Saamu124yor_bib
Orin fún ìgòkè. Ti Dafidi.
1“Ìbá má ṣe pé Olúwa tí ó ti wà fún wa,”kí ni Israẹli kí ó máa wí nísinsin yìí;2ìbá má ṣe pé Olúwa tó wà ní tiwa,nígbà tí àwọn ènìyàn gbógun sí wa,3nígbà náà ni wọn ò bá gbé wà mì láààyènígbà tí ìbínú wọn ru sí wa,4nígbà náà ni omiwọ̀n-ọn-nì ìbá bò wá mọ́lẹ̀,5nígbà náà ni agbéragaomi ìbá borí ọkàn wa.6Olùbùkún ni Olúwa, tí kò fi wá fún wọ́nbí ohun ọdẹ fún eyín wọn.7Ọkàn wa yọ bí ẹyẹ jáde kúrò nínú okùn apẹyẹ;okùn já àwa sì yọ.8Ìrànlọ́wọ́ wa ń bẹ ní orúkọ Olúwa,tí ó dá ọ̀run òun ayé.