Saamu107yor_bib
1Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun;nítorí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.2Jẹ́ kí àwọn ẹni ìràpadà Olúwa kí ó wí báyìí,àwọn ẹni tí ó rà padà kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá,3àwọn tí ó kójọ láti ilẹ̀ wọ̀n-ọn-nì,láti ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn,láti àríwá àti Òkun wá.4Wọ́n ń rìn káàkiri ní aginjù ní ibi tí ọ̀nà kò sí,wọn kò rí ọ̀nà lọ sí ìlú níbi tíwọn ó máa gbé.5Ebi ń pa wọn, òǹgbẹ gbẹ wọ́n,ó sì rẹ ọkàn wọn nínú wọn.6Ní ìgbà náà, wọ́n kígbe sókèsí Olúwa nínú ìdààmú wọn,ó sì yọ wọ́n kúrò nínú ìrora wọn7Ó fi ọ̀nà títọ́ hàn wọ́n sí ìlútí wọn lè máa gbé.8Ẹ jẹ́ kí wọn máa yin Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ìyanu rẹ̀ sí àwọn ọmọ ènìyàn,9nítorí tí ó tẹ́ ìfẹ́ ọkàn lọ́runó sì fi ìre fún ọkàn tí ebi ń pa.10Ọ̀pọ̀ jókòó nínú òkùnkùn àti òjìji ikú,a dè wọ́n ní ìrora àti ní irin,11nítorí tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀Ọlọ́run, wọ́n kẹ́gàn ìbáwí Ọ̀gá-ògo,12Ó sì fi ìkorò rẹ àyà wọn sílẹ̀;wọn ṣubú, kò sì ṣí ẹni tíyóò ràn wọ́n lọ́wọ́.13Ní ìgbà náà wọ́n ké peOlúwa nínú ìdààmú wọn,ó sì gbà wọ́n nínú ìṣòro wọn14Ó mú wọn jáde kúrò nínúòkùnkùn àti òjìji ikú,ó sì fa irin tí wọ́n fi dè wọ́n já.15Ẹ jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa! Nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí ọmọ ènìyàn.16Nítorí tí ó já ìlẹ̀kùn idẹ wọ̀n-ọn-nìó sì ké irin wọn ní agbede-méjì.17Ọ̀pọ̀ di aṣiwèrè nítorí ìrékọjá wọnwọ́n sì pọ́n wọn lójú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.18Wọ́n kọ gbogbo oúnjẹwọ́n sì súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú.19Nígbà náà wọ́n kígbe sí Olúwa nínú ìṣòro wọn,ó sì yọ wọ́n nínú ìdààmú wọn.20Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀, ara wọn sì dáó sì yọ wọ́n nínú isà òkú.21Ẹ jẹ́ kí wọ́n fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.22Jẹ́ kí wọn rú ẹbọ ọpẹ́kí wọn kí ó fi ayọ̀ sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ̀.23Àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí Òkun nínú ọkọ̀ ojú omi,wọ́n jẹ́ oníṣòwò nínú omi ńlá.24Wọ́n rí iṣẹ́ Olúwa,àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ nínú ibú.25Nítorí tí ó pàṣẹ, ó sì mú ìjì fẹ́tí ó gbé ríru rẹ̀ sókè.26Wọ́n gòkè lọ sí ọ̀run wọ́n sìtún sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibú:nítorí ìpọ́njú, ọkàn wọn di omi.27Wọ́n ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n bí ọ̀mùtí ènìyàn:ọgbọ́n wọn sì dé òpin.28Nígbà náà wọ́n ń kígbe sókèsí Olúwa nínú ìdààmú wọn,ó sì mú wọn jáde nínú ìṣòro wọn.29Ó sọ ìjì di ìdákẹ́rọ́rọ́bẹ́ẹ̀ ni ríru omi rẹ̀ dúró jẹ́ẹ́.30Inú wọn dùn nígbà tí ara wọn balẹ̀,ó mú wọn lọ sí ibi tí ọkàn wọn lọ.31Jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fúnOlúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.32Jẹ́ kí wọn gbé e ga ní àárín àwọn ènìyànkí wọn kí ó sì yìn ín ní ìjọ àwọn àgbàgbà.33Ó sọ odò di aginjù,àti orísun omi di ilẹ̀ gbígbẹ.34Ilẹ̀ eléso di aṣálẹ̀nítorí ìwà búburú àwọn tí ó wà nínú rẹ̀.35O sọ aginjù di adágún omi àtiilẹ̀ gbígbẹ di orísun omi,36níbẹ̀ ó mú ẹni tí ebi ń pa wà,wọ́n sì pilẹ̀ ibi tí wọn ó máa gbé.37Wọn fún irúgbìn, wọ́n sì gbin ọgbà àjàràtí yóò máa so èso tí ó dára;38Ó bùkún wọn, wọ́n sì pọ̀ sí i ní iyekò sí jẹ́ kí ẹran ọ̀sìn wọn kí ó dínkù.39Nígbà náà, ọjọ́ wọn kúrú,ìnira, ìpọ́njú àti ìṣòro wọn sì dínkù,40ẹni tí ó da ẹ̀gàn lu ọmọ-aládéó sì mú wọn rìn níbi tí ọ̀nà kò sí.41Ṣùgbọ́n ó gbé aláìní sókè kúrò nínú ìniraó mú ìdílé wọn pọ̀ bí agbo ẹran.42Àwọn tí ó dúró sì rí i, inú wọn sì dùnṣùgbọ́n gbogbo olùṣe búburú yóò pa ẹnu rẹ̀ mọ́.43Ẹni tí ó bá gbọ́n, jẹ́ kí ó kíyèsi nǹkan wọ̀nyíkí ó wo títóbi ìfẹ́ Olúwa.