Jobu36yor_bib
1Elihu sì tún sọ̀rọ̀ wí pé,2“Fún mi láyè díẹ̀ èmi ó sì fihàn ọ́,nítorí ọ̀rọ̀ sísọ ní ó kún fún Ọlọ́run.3Èmi ó mú ìmọ̀ mi ti ọ̀nà jíjìn wá,èmi ó sì fi òdodo fún Ẹlẹ́dàá mi.4Rí i dájú pé ọ̀rọ̀ mi kì yóò ṣèké nítòótọ́;ẹni tí ó pé ní ìmọ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.5“Kíyèsi i, Ọlọ́run ni alágbára, òun kò i sì gàn ènìyàn;ó ní agbára ní ipá àti òye.6Òun kì í dá ẹ̀mí ènìyàn búburú sí,ṣùgbọ́n ó fi òtítọ́ fún àwọn tálákà.7Òun kì í mú ojú rẹ̀ kúrò lára olódodo,ṣùgbọ́n àwọn ọba ni wọ́n wà lórí ìtẹ́;àní ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé, a sì gbé wọn lékè.8Bí ó bá sì dè wọ́n nínú àbà,tí a sì fi okùn ìpọ́njú dè wọ́n,9nígbà náà ni ó ń sọ àwọn ohun tí wọn ti ṣe fún wọn,wí pé wọ́n ti ṣẹ̀ pẹ̀lú ìgbéraga wọn.10Ó sí wọn létí pẹ̀lú sí ọ̀nà ẹ̀kọ́,ó sì pàṣẹ kí wọn kí ó padà kúrò nínú àìṣedédé.11Bí wọ́n bá gbàgbọ́ tí wọ́n sì sìn ín,wọn ó lo ọjọ́ wọn ní ìrọ̀rùn,àti ọdún wọn nínú afẹ́.12Ṣùgbọ́n, bí wọn kò bá gbàgbọ́,wọ́n ó ti ọwọ́ idà ṣègbé,wọ́n á sì kú láìní òye.13“Ṣùgbọ́n àwọn àgàbàgebè ní ayé kó ìbínú jọ;wọn kò kígbe fún ìrànlọ́wọ́ nígbà tí ó bá wọ́n wí.14Nígbà náà ni ọkàn wọn yóò kú ní èwe,ní àárín àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà.15Òun gba òtòṣì nínú ìpọ́njú wọn,a sì sọ̀rọ̀ sí wọn ní etí nínú ìnira wọn.16“Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lúpẹ̀lú ó fa wọn yọ láti inú ìhágágá sí ibi gbòòrò,sí ibi tí ó ní ààyè tí kò ní wàhálà nínú rẹ̀,ohun tí a sì gbé kalẹ̀ ní tábìlì rẹ̀ jẹ́ kìkì ọ̀rá oúnjẹ tí ó fẹ́.17Ṣùgbọ́n ìwọ kún fún ìdájọ́ àwọn búburú;ìdájọ́ àti òtítọ́ dì ọ́ mú.18Nítorí ìbínú ń bẹ, ṣọ́ra kí òtítọ́ rẹ máa bá a tàn ọ;láti jẹ́ kí títóbi rẹ mú ọ ṣìnà.19Ọrọ̀ rẹ pọ̀ tó, tí wàhálà kì yóò fi dé bá ọ bí?Tàbí ipa agbára rẹ?20Má ṣe ìfẹ́ òru, nígbà tí a ń kéàwọn orílẹ̀-èdè kúrò ní ipò wọn.21Máa ṣọ́ra kí ìwọ ki ó má yí ara rẹ̀ padà sí búburú,nítorí èyí tí ìwọ rò pé ó dára jù ìpọ́njú lọ.22“Kíyèsi i, Ọlọ́run ni gbéga nípa agbára rẹ̀;ta ni jẹ́ olùkọ́ni bí rẹ̀?23Ta ni ó là ọ̀nà iṣẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ fún un,tàbí ta ni ó lè wí pé ìwọ ti ń ṣe àìṣedéédéé?24Rántí kí ìwọ kí ó gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga,ti ènìyàn ni yín nínú orin.25Olúkúlùkù ènìyàn a máa rí i;ẹni ikú a máa wò ó ní òkèrè.26Kíyèsi i, Ọlọ́run tóbi, àwa kò sì mọ̀ bí ó ti ní òye tó,bẹ́ẹ̀ ni a kò lè wádìí iye ọdún rẹ̀ rí.27“Nítorí pé òun ni ó fa ìkán omi òjò sílẹ̀,kí wọn kí ó kán bí òjò ní ìkùùkuu rẹ̀,28tí àwọsánmọ̀ ń rọ̀ ìrì rẹ̀ sílẹ̀,tí ó sì fi ń sẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ lórí ènìyàn.29Pẹ̀lúpẹ̀lú ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè ní ìmọ̀ ìtànká àwọsánmọ̀,tàbí ariwo àrá láti àgọ́ rẹ̀?30Kíyèsi i, ó tan ìmọ́lẹ̀ yí ara rẹ̀ káó sì bo ìsàlẹ̀ òkun mọ́lẹ̀.31Nítorí pé nípa wọn ní ń ṣe dájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ènìyàn;ó sí ń pèsè oúnjẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.32Ó fi ìmọ́lẹ̀ bo ọwọ́ rẹ̀ méjèèjìó sì rán an sí ẹni olódì.33Ariwo àrá rẹ̀ fi ìjì hàn ní;ọ̀wọ́ ẹran pẹ̀lú wí pé, ó súnmọ́ etílé!