Jeremiah4yor_bib
1“Tí ìwọ yóò bá yí padà, ìwọ Israẹli, padà tọ̀ mí wá,”ni Olúwa wí.“Tí ìwọ yóò bá sì mú ìríra rẹ kúrò níwájú mi,ìwọ kí ó sì rìn kiri.2Tí ó bá jẹ́ lóòtítọ́ àti òdodo ni ìwọ búra.Nítòótọ́ bí Olúwa ti wà láààyè,nígbà náà ni orílẹ̀-èdè yóò di alábùkún fún nípasẹ̀ rẹ,àti nínú rẹ̀ ni wọn yóò ṣògo.”3Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu:“Hú gbogbo ilẹ̀ tí ẹ kò lò rí,kí o má sì ṣe gbìn sáàrín ẹ̀gún.4Kọ ara rẹ ní ilà sí Olúwa,kọ ọkàn rẹ ní ilà,ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu,bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú mi yóò ru jáde yóò sì jó bí iná,nítorí ibi tí o ti ṣekì yóò sí ẹni tí yóò pa á.