1Nítorí Sioni èmi kì yóò dákẹ́,nítorí i Jerusalẹmu èmi kì yóò sinmi ẹnu,títí tí òdodo rẹ̀ yóò fi tàn bí òwúrọ̀,àti ìgbàlà rẹ̀ bí i fìtílà tí ń jó geere.2Àwọn orílẹ̀-èdè yóò rí òdodo rẹ,àti gbogbo ọba ògo rẹa ó sì máa pè ọ́ ní orúkọ mìírànèyí tí ẹnu Olúwa yóò fi fún un.3Ìwọ yóò sì jẹ́ adé dídán ní ọwọ́ Olúwa,adé ọba ní ọwọ́ Ọlọ́run rẹ.4Wọn kì yóò pè ọ́ ní ìkọ̀sílẹ̀ mọ́tàbí kí wọ́n pe ilẹ̀ rẹ ní ahoro.Ṣùgbọ́n a ó máa pè ọ́ ní Hẹfsiba,àti ilẹ̀ rẹ ní Beula;nítorí Olúwa yóò yọ́nú sí ọàti ilẹ̀ rẹ ni a ó gbé níyàwó.5Gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́mọkùnrin tí í gbé ọ̀dọ́mọbìnrin níyàwó,bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọkùnrin rẹ yóò gbé ọ níyàwóGẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ṣe é yọ̀ lórí ìyàwó rẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run rẹ yóò yọ̀ lórí rẹ.6Èmi ti fi olùṣọ́ ránṣẹ́ sórí odi rẹ ìwọ Jerusalẹmu;wọn kì yóò lè dákẹ́ tọ̀sán tòru.Ẹ̀yin tí ń ké pe Olúwa,ẹ má ṣe fúnra yín ní ìsinmi,7àti kí ẹ má ṣe fún òun pẹ̀lú ní ìsinmitítí tí yóò fi fi ìdí Jerusalẹmu múlẹ̀tí yóò sì fi ṣe ìyìn orí ilẹ̀ ayé.8Olúwa ti búra pẹ̀lú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀àti nípa agbára apá rẹ:“Èmi kì yóò jẹ́ kí ìyẹ̀fun rẹdi oúnjẹ fún ọ̀tá rẹbẹ́ẹ̀ ni àwọn àjèjì kì yóò mu wáìnìtuntun rẹ mọ́èyí tí ìwọ ti ṣe làálàá fún;9ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá kóórè rẹ̀ ni yóò jẹ ẹ́,tí wọn ó sì yin Olúwa,àti àwọn tí wọ́n bá kó àjàrà jọ ni wọn ó mú un,nínú àgbàlá ilé mímọ́ mi.”10Ẹ kọjá, ẹ kọjá ní ẹnu ibodè náà!Ẹ tún ọ̀nà ṣe fún àwọn ènìyàn.Ẹ mọ ọ́n sókè, ṣe ojú ọ̀nà òpópó!Ẹ ṣa òkúta kúrò.Ẹ gbé àsíá sókè fún àwọn orílẹ̀-èdè.11Olúwa ti ṣe ìkédetítí dé òpin ilẹ̀ ayé:“Ẹ sọ fún ọmọbìnrin Sioni pé,‘Kíyèsi i, Olùgbàlà rẹ ń bọ̀!Kíyèsi i, èrè ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀,àti ẹ̀san rẹ̀ pẹ̀lú n tẹ̀lé e lẹ́yìn.’ ”12A ó sì pè wọ́n ní Ènìyàn Mímọ́,ẹni ìràpadà Olúwa;a ó sì máa pè ọ́ ní ìwákiri,ìlú tí a kì yóò kọ̀sílẹ̀.