Hosea7yor_bib
1nígbà tí èmi ìbá mú Israẹli láradá.Ẹ̀ṣẹ̀ Efraimu ń farahànìwà búburú Samaria sì ń hàn síta.Wọ́n ń ṣe ẹ̀tàn,àwọn olè ń fọ́ ilé;àwọn ọlọ́ṣà ń jalè ní òpópónà;2ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀ pémo rántí gbogbo ìwà búburú wọn.Ẹ̀ṣẹ̀ wọn gbé wọn mì pátápátá;wọ́n wà níwájú mi nígbà gbogbo.3“Wọ́n ń mú inú ọba dùn pẹ̀lú ìwà búburú wọn,àti inú ọmọ-aládé dùn pẹ̀lú irọ́ wọn.4Alágbèrè ni gbogbo wọnwọ́n gbóná bí ààrò àkàràtí a dáwọ́ kíkoná dúró,lẹ́yìn ìgbà tí o ti pò ìyẹ̀fun tán, títí ìgbà tí yóò wú.5Ní ọjọ́ àjọ̀dún ọba wawáìnì mú ara ọmọ-aládé gbónáó sì darapọ̀ mọ́ àwọn oníyẹ̀yẹ́.6Ọkàn wọn ń gbóná bí i ààròwọ́n sì tọ̀ ọ́ lọ pẹ̀lú rìkíṣí,ìbínú wọn pa lọ́lọ́ ní gbogbo òruó sì bú jáde bí ọ̀wọ́-iná ní òwúrọ̀.7Gbogbo wọn gbóná bí ààròwọ́n pa gbogbo olórí wọn run,gbogbo ọba wọn si ṣubúkò sì ṣí ẹnìkan nínú wọn tí ó ké pè mí.8“Efraimu ti darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn náà;Efraimu jẹ́ àkàrà tí a kò yípadà.9Àwọn àlejò ti jẹ agbára rẹ̀ runṣùgbọ́n kò sì mọ̀.Ewú ti wà ní orí rẹ̀ káàkiribẹ́ẹ̀ ni kò kíyèsi i.10Ìgbéraga Israẹli ń jẹ́rìí sí iṣùgbọ́n pẹ̀lú gbogbo èyíkò padà sí ọ̀dọ̀ OlúwaỌlọ́run, tàbí kí ó wá a.11“Efraimu dàbí àdàbàtó rọrùn láti tànjẹ àti aláìgbọ́ntó wá ń pé Ejibiti nísinsin yìító sì tún ń padà lọ si Asiria.12Nígbà tí wọ́n bá lọ, èmi ó ta àwọ̀n mi sórí wọn,Èmi ó fà wọ́n lulẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ ojú ọ̀run.Nígbà tí mo bá gbọ́ pé wọ́n rìn pọ̀,Èmi ó nà wọ́n fún iṣẹ́ búburú ọwọ́ wọn.13Ègbé ní fún wọn,nítorí pé wọ́n ti yà kúrò lọ́dọ̀ mi!Ìparun wà lórí wọn,nítorí pé wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi!Èmi fẹ́ láti rà wọ́n padà.Ṣùgbọ́n wọ́n ń parọ́ mọ́ mi.14Wọn kò kégbe pè mí láti ọkàn wọn,ṣùgbọ́n wọ́n ń pohùnréré ẹkún lórí ibùsùn wọn.Wọ́n kó ara wọn jọ, nítorí ọkà àti wáìnìṣùgbọ́n wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.15Mo kọ́ wọn, mo sì fún wọn ní agbára,síbẹ̀ wọ́n tún ń dìtẹ̀ mọ́ mi.16Wọn kò padà sí ọ̀dọ̀ Ọ̀gá-ògo;wọ́n dàbí ọfà tí ó ti bàjẹ́.Àwọn aṣíwájú wọn yóò ti ipa idà ṣubúnítorí ìrunú ahọ́n wọn.Torí èyí, wọn ó fi wọ́n ṣeẹlẹ́yà ní ilẹ̀ Ejibiti.