1“Nígbà tí Israẹli wà ní ọmọdé mo fẹ́ràn rẹ̀,mo sì pe ọmọ mi jáde láti Ejibiti wá.2Bí a ti ń pe wọn,bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń sá kúrò lọ́dọ̀ mi,wọn rú ẹbọ sí Baali,wọn sì fi tùràrí jóná sí ère fínfín.3Lóòtítọ́ mo kọ́ Efraimu pẹ̀lú ní ìrìnmo di wọ́n mú ní apá,ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀pé mo ti mú wọn láradá.4Mo fi okùn ènìyàn fà wọ́nàti ìdè ìfẹ́.Mo mú àjàgà kúrò ni ọrùn wọn,Mo sì fi ara balẹ̀ fún wọn ni oúnjẹ.5“Ṣé wọn ò wá ní padà sí Ejibiti bí.Ṣé Asiria kò sì ní jẹ ọba lé wọn lórí bínítorí pé wọ́n kọ̀ jálẹ̀ láti ronúpìwàdà?6Idà yóò kọ mọ̀nà ní gbogbo ìlú wọnyóò si bá gbogbo irin ẹnu odi ìlú wọn jẹ́yóò sì fi òpin sí gbogbo èrò wọn.7Àwọn ènìyàn mi ti pinnu láti pẹ̀yìndà kúrò lọ́dọ̀ mibí wọ́n tilẹ̀ pè wọ́n sọ́dọ̀ Ọ̀gá-ògo jùlọ,kò ní gbé wọn ga rárá.8“Báwo ni èmi ó ṣe fi ọ́ sílẹ̀, Efraimu?Báwo ni èmi ó ṣe yọ̀ǹda rẹ̀, Israẹli?Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Adma?Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Seboimu?Ọkàn mi yípadà nínú miàánú mi sì ru sókè.9Èmi kò ni mú ìbínú gbígbóná mi ṣẹ,tàbí kí èmi wá sọ Efraimu di ahoro.Nítorí pé èmi ni Ọlọ́run, àní, èmi kì í ṣe ènìyàn.Ẹni mímọ́ láàrín yín,Èmi kò ní í wá nínú ìbínú.10Wọn yóò máa tẹ̀lé Olúwa;òun yóò bú ramúramù bí i kìnnìún.Nígbà tó bá bú,àwọn ọmọ rẹ yóò wá ní ìwárìrì láti ìwọ̀-oòrùn.11Wọn ó wá pẹ̀lú ẹ̀rùbí i ẹyẹ láti Ejibiti,bí i àdàbà láti Asiria,Èmi ó mú wọn padà sí ilé wọn,”ni Olúwa wí.
Ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli
12Efraimu tí fi irọ́ yí mi káilé Israẹli pẹ̀lú ẹ̀tàn.Ṣùgbọ́n Juda sì dúró ṣinṣin pẹ̀lú Ọlọ́run.Ó sì ṣe olóòtítọ́ sí Ẹni mímọ́ Israẹli.