Amosi2yor_bib
1Èyí ni ohun tí Olúwa wí,“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Moabu,àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà,nítorí ó ti sun ún, di eérú,egungun ọba Edomu,2Èmi yóò rán iná sí orí Moabuèyí tí yóò jó àwọn ààfin Kerioti run.Moabu yóò sì kú pẹ̀lú ariwopẹ̀lú igbe àti pẹ̀lú ìró ìpè.3Èmi yóò ké onídàájọ́ rẹ̀ kúrò,Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn ọmọ-aládé rẹ́ nínú rẹ̀,”ni Olúwa wí.4Èyí ni ohun tí Olúwa wí,“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Juda,àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà.Nítorí wọn ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀,wọn kò sì pa àwọn ìlànà rẹ̀ mọ́.Nítorí àwọn òrìṣà ti sì wọ́n lọ́nà,òrìṣà tí àwọn Baba ńlá wọn ń tẹ̀lé,5Èmi yóò rán iná sí orí Judaèyí tí yóò jó àwọn ààfin Jerusalẹmu run.”